Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

2 Kọ́ríńtì 11:16-33 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. Mo sì tún wí pé, kí ẹnikẹ́ni má ṣe rò pé òmùgọ̀ ni mí; ṣùgbọ́n bí bẹ́ẹ̀ bá ni, ẹ gbà mí bí òmùgọ̀ kí èmi lè gbé ara mi ga díẹ̀.

17. Ohun tí èmi ń sọ, èmi kò sọ ọ́ nípa ti Olúwa, ṣùgbọ́n bí òmùgọ̀ nínú ìgbẹ́kẹ̀lé ìṣògo yìí.

18. Ọ̀pọ̀lọpọ̀, ni ó ń ṣògo nípa ti ara, èmi ó ṣògo pẹ̀lú.

19. Nítorí ẹ̀yin fi inú dídùn gba àwọn òmùgọ̀ nígbà tí ẹ̀yin tìkáraayín jẹ́ ọlọgbọ́n.

20. Nítorí ẹ̀yin faradà á bí ẹnìkan bá sọ yín dí òǹdè, bí ẹnìkan bá jẹ́ yín run, bí ẹnìkan bá gbà lọ́wọ́ yín, bí ẹnìkan bá gbé ara rẹ̀ ga, bí ẹnìkan bá gbá yín lójú.

21. Èmi ń wí lọ́nà ẹ̀gàn, bí ẹni pé àwa jẹ́ aláìlera!Ṣùgbọ́n nínú ohunkóhun tí ẹnìkan ti ní ìgboyà, èmi ń sọ̀rọ̀ bí òmùgọ̀, èmi ní ìgboyà pẹ̀lú.

22. Hébérù ni wọ́n bí? Bẹ́ẹ̀ ni èmi. Ísírẹ́lì ni wọ́n bí? Bẹ́ẹ̀ ni èmi. Irú ọmọ Ábúráhámù ní òun bí? Bẹ́ẹ̀ ni èmi.

23. Iránṣẹ́ Kírísítì ni wọ́n bí? Èmi ń sọ bí òmùgọ̀, mo ta wọ́n yọ; ní ti làálàá lọ́pọ̀lọpọ̀, ní ti pàṣán, mo rékọjá, ní ti túbú nígbákùúgbà, ní ti fífẹ́rẹ̀ kú nígbà púpọ̀.

24. Nígbà márùn-ún ni mo gba pàṣán ogójì dín kan lọ́wọ́ àwọn Júù.

25. Nígbà mẹ́ta ni a fi ọ̀gọ̀ lù mí, ẹ̀ẹ̀kanṣoṣo ni a sọ mí ní òkúta, ẹ̀ẹ̀mẹ́ta ni ọkọ̀ ojú omi mi rì, ọ̀sán kan àti òru kan ni mo wà nínú ibú.

26. Ní ìrìnàjò nígbákùúgbà, nínú ewu omi, nínú ewu àwọn ọlọ́ṣà, nínú ewu àwọn ará ìlú mi, nínú ewu àwọn aláìkọlà, nínú ewu ni ìlú, nínú ewu ní ihà, nínú ewu lójú òkun, nínú ewu láàárin àwọn èké arákùnrin.

27. Nínú làálàá àti ìrora, nínú ìṣọ́-òru nígbákùúgbà, nínú ebi àti òrùgbẹ, nínú ààwẹ̀ nígbákùúgbà, nínú òtútù àti ìhòòhò.

28. Pẹ̀lú nǹkan wọ̀nyí tí ó jẹ́ tí òde, ọ̀pọ̀ ni èyí tí ń wọ́ jọ tì mí lójoojúmọ́, àní àníyàn fún gbogbo ìjọ.

29. Ta ni ó ṣe àìlera, tí èmi kò ṣe àìlera? Tàbí a mú kọsẹ̀, tí ara mi kò gbiná?

30. Bí èmi yóò bá ṣògo, èmi ó kúkú máa ṣògo nípa àwọn nǹkan tí ó jẹ́ ti àìlera mi.

31. Ọlọ́run àti Baba Olúwa wá Jésù Kírísítì, ẹni tí ó jẹ́ olùbùkún jùlọ láéláé mọ̀ pé èmi kò ṣèké.

32. Ní Dámásíkù, baálẹ̀ tí ó wà lábẹ́ ọba Árétà fí ẹgbẹ́ ogun ká ìlú àwọn ara Dámásíkù mọ́, ó ń fẹ́ mi láti mú:

33. Láti ojú fèrèsé nínú agbọ̀n ni a sì ti sọ̀ mí kalẹ̀ lẹ́yìn odi, tí mo sì bọ́ lọ́wọ́ rẹ̀.

Ka pipe ipin 2 Kọ́ríńtì 11