Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kọ́ríńtì 9:6-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Ṣé kìkì Bánábà àti èmi ló yẹ kí a máa ṣisẹ́ bọ́ ara wa ni?

7. Ta ni ó síṣẹ́ ogun nígbà tí ó sanwo ara rẹ̀? Ta ní gbin ọgbà àjàrà tí kì í jẹ nínú èso rẹ̀?, Tàbí ta ní ń bọ ọ̀wọ́-ẹran tí kì í sí ì jẹ nínú wàrà ọ̀wọ́-ẹran?

8. Èmi ha sọ nǹkan wọ̀nyí bí ènìyàn? Tàbí òfin kò wí bákan náà bì?

9. Nítorí nínú òfin tí Ọlọ́run fún Mósè, ni a tí kọ ọ́ pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ di màlúù ti ń pakà nínú oko rẹ̀ lẹ́nu mọ́.” Ǹjẹ́ màlúù ni Ọlọ́run n ṣe ìtọ́jú rẹ̀ bi?

10. Dájúdájú ó sọ eléyìí fún wa pé, nítorí wa ni a se kọ̀wé yìí kí ẹni tí ń tulẹ̀ lè máa tulẹ̀ ní ìrètí àti ẹni tí ń pakà lè ni ìretí láti ní ipin nínú ìkórè.

Ka pipe ipin 1 Kọ́ríńtì 9