Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kọ́ríńtì 15:27-30 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

27. “Nítorí ó ti fí ohun gbogbo sábẹ́ ẹṣẹ̀ rẹ̀.” Ṣùgbọ́n nígbà tí ó wí pé, “Ohun gbogbo ni á fí sí abẹ́ rẹ̀,” o dájú pé Ọlọ́run nìkanṣoṣo ní kò sí ní abẹ́ rẹ̀, Òun ní ó fí ohun gbogbo sí abẹ́ àkóso Kírísítì.

28. Nígbà tí a bá sì fi ohun gbogbo sí abẹ́ rẹ̀ tán, nígbà náà ni á ó fi ọmọ tìkárarẹ̀ pẹ̀lú sábẹ́ Ẹni tí ó fí ohun gbogbo sí abẹ́ rẹ̀, kí Ọlọ́run lè jásí ohun gbogbo nínú ohun gbogbo.

29. Ní báyìí, bí kò bá sí àjíǹde, kín ní ète àwọn ènìyàn tí wọn ń tẹ bọmi nítorí òkú? Bí àwọn òkú kò bá jíǹde rárá, nítorí kín ni a ṣe ń bamítíìsì wọn nítorí wọn?

30. Nítorí kínní àwa sì ṣe ń bẹ nínú ewu ni wákàtí gbogbo?

Ka pipe ipin 1 Kọ́ríńtì 15