Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

1 Kọ́ríńtì 15:24-37 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

24. Nígbá náà ni òpín yóò dé, nígbà tí ó bá ti fi ìjọba fún Ọlọ́run Baba, nígbà tí ó bá pá gbogbo àṣẹ àti gbogbo ọlá àti agbára run.

25. Nítorí ti òun gbọdọ̀ ti jọba kí òun to fí gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀ sí abẹ́ ẹṣẹ̀ rẹ̀.

26. Ikú ní ọ̀ta ìkẹ́yìn tí a ó párun

27. “Nítorí ó ti fí ohun gbogbo sábẹ́ ẹṣẹ̀ rẹ̀.” Ṣùgbọ́n nígbà tí ó wí pé, “Ohun gbogbo ni á fí sí abẹ́ rẹ̀,” o dájú pé Ọlọ́run nìkanṣoṣo ní kò sí ní abẹ́ rẹ̀, Òun ní ó fí ohun gbogbo sí abẹ́ àkóso Kírísítì.

28. Nígbà tí a bá sì fi ohun gbogbo sí abẹ́ rẹ̀ tán, nígbà náà ni á ó fi ọmọ tìkárarẹ̀ pẹ̀lú sábẹ́ Ẹni tí ó fí ohun gbogbo sí abẹ́ rẹ̀, kí Ọlọ́run lè jásí ohun gbogbo nínú ohun gbogbo.

29. Ní báyìí, bí kò bá sí àjíǹde, kín ní ète àwọn ènìyàn tí wọn ń tẹ bọmi nítorí òkú? Bí àwọn òkú kò bá jíǹde rárá, nítorí kín ni a ṣe ń bamítíìsì wọn nítorí wọn?

30. Nítorí kínní àwa sì ṣe ń bẹ nínú ewu ni wákàtí gbogbo?

31. Mo sọ nípa ayọ̀ tí mo ní lórí yín nínú Kírísítì Jésù Olúwa wá pé, èmi ń kú lojoojúmọ.

32. Kí a wí bí ènìyàn, bí mo bá ẹranko jà ní Éfésù, àǹfàání kín ni ó jẹ́ fún mi? Bí àwọn òkú kò bá jínde,“Ẹ jẹ́ kí a máa jẹ kí á máa mú;nítorí ní ọlá ni àwa ó kú.”

33. Kí a má tàn yín jẹ́: “Ẹgbẹ́ búburú bá ìwà rere jẹ́!?”

34. Ẹ ji ìjí òdodo, kí ẹ má sì dẹ́ṣẹ̀; nítorí àwọn ẹlómírán kò ni imọ̀ Ọlọ́run: mo sọ èyí kí ojú baà lè ti yín.

35. Ṣùgbọ́n ẹnìkan yóò wí pé, “Báwo ni àwọn òkú yóò ṣe jíǹde? Irú ara wó ni wọn ó padà sí?”

36. Iwọ aláìmòye, ohun tí ìwọ fúnrúgbìn kì í yè bí kò ṣe pé ó kú:

37. Àti èyí tí ìwọ fúnrúgbìn, kì í ṣe ara tí ń bọ̀ ni ìwọ fúnrúgbìn, ṣùgbọ́n irúgbín lásán ni, ìbáàṣe àlìkámà, tabi irú mìíràn.

Ka pipe ipin 1 Kọ́ríńtì 15