Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sekaráyà 11:15-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Olúwa sì wí fún mi pé, “Tún mú ohun-èlò Olùṣọ́-àgùntàn búburú kan ṣọ́dọ̀ rẹ̀.

16. Nítorí Èmi o gbé olùṣọ́-àgùntàn kan dídé ni ilẹ̀ náà, tí kí yóò bẹ àwọn tí ó ṣègbé wò, ti kì yóò sì wá èyí tí ó yapa; tí kì yóò ṣe ìtọ́jú èyí tí a pa lára tàbí kí ó bọ́ àwọn tí ara wọn dá pépé: Ṣùgbọ́n òun yóò jẹ ẹran èyi tí ó ni ọ̀rá, yóò sì fa èékánna wọn ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ.

17. “Ègbé ni fún olùṣọ́-àgùntàn aṣán náà,tí ó fi ọ̀wọ́-ẹran sílẹ́!Idà yóò ge apá rẹ̀ àti ojú ọ̀tún rẹ̀:apá rẹ̀ yóò gbẹ pátapáta,ojú ọ̀tún rẹ̀ yóò sì fọ́ pátapáta!”

Ka pipe ipin Sekaráyà 11