Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 96:7-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Ẹ fi fún Olúwa, ẹ yin ìbátan ènìyànẸ fi agbára àti ògo fún Olúwa

8. Ẹ fi ògo tí o tọ́ sí Olúwa fún un;ẹ mú ọrẹ wá, kí ẹ sì wá sí àgbàlá Rẹ̀

9. Ẹ máa sin Olúwa ninú ẹwà ìwà mímọ́ Rẹ̀;ẹ wárìrì níwájú Rẹ̀ gbogbo ayé.

10. Sọ láàrin àwọn orílẹ̀ èdè, “Olúwa jọbaa fi ìdí ayé mú lẹ̀, tí kò sì lè yí;ẹni tí yóò fi òtítọ́ ṣe ìdájọ́ ènìyàn.”

11. Jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó yọ̀, kí ayé sì dùnjẹ́ kí òkun kí ó hó pẹ̀lú ohungbogbo tí ń bẹ nínú Rẹ̀.

12. Jẹ́ kí oko kún fún ayọ̀àti ohun gbogbo ti ń bẹ nínú Rẹ̀:nígbà náà ni gbogbo igi igbó yóò máa yọ̀

13. Wọn yóò kọrin níwájú Olúwa,nítorí ti ó ń bọ́ wá,òun bọ̀ wá ṣe ìdájọ́ ayéyóò fi òdodo ṣe ìdájọ́ ayéàti ti àwọn ènìyàn ni yóò fí òtítọ́ Rẹ̀ ṣe.

Ka pipe ipin Sáàmù 96