Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 92:8-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa ni a ó gbéga títí láé.

9. Nítorí nítòótọ́ àwọn ọ̀tá Rẹ, Olúwa,nítòótọ́ àwọn ọ̀ta Rẹ yóò ṣègbé;gbogbo àwọn olùṣe búburúní a ó fọ́nká.

10. Ìwọ tí gbé ìwo mi ga bí i ti màlúù igbó;òróró dídára ni a dà sími ní orí.

11. Ojú mi ti rí ìṣubú àwọn ọ̀ta mi;ìparun sí àwọn ènìyàn búburútí ó dìde sí mi.

12. Olódodo yóò gbèrú bí i igi ọ̀pẹ,wọn yóò dàgbà bí i igi kédárì Lẹ́bánónì;

13. Tí a gbìn si ilé Olúwa,Wọn yóò rúwé nínú àgbàlá Ọlọ́run wa.

14. Wọn yóò máa so èso ní ìgbà ogbówọn yóò dúró ní àkọ̀tun, wọn yóò sì tutù nini,

Ka pipe ipin Sáàmù 92