Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 9:8-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Òun yóò sì ṣe ìdájọ́ àyé ní òdodo;yóò ṣe àkóso ènìyàn pẹ̀lú òdodo.

9. Olúwa ni ààbò fún àwọn tí a ni lára,ibi ìsádi ní àkókò ìpọ́njú.

10. Àwọn tí ó mọ orúkọ Rẹ yóò gbà ọ́ gbọ́,èmi tàbí ìwọ, Olúwa, kò kọ àwọn to ń wa a sílẹ̀.

11. Kọ orin ìyìn sí Olúwa, ti o ń jọba ní Síónì;kéde láàrin àwọn orílẹ̀ èdè ohun tí o ṣe.

12. Nítorí ẹni tí ó ń gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ rántí;òun kò kọ ẹkún àwọn tí a pọ́n lójú.

13. Olúwa, wo bí àwọn ọ̀ta ṣe ń ṣe inúnibíni sí mi!Ṣàánú, kí o sì gbé mí sókè kúrò ní ẹnu ọ̀nà ikú,

14. Kí èmi kí o lè sọ ti ìyìn Rẹni ẹnu ọ̀nà àwọn ọmọbìnrin Síónìàti láti máa yọ̀ nínú ìgbàlà Rẹ.

15. Àwọn orílẹ̀ èdè ti jìn sí kòtò ti wọn ti gbẹ́;ẹsẹ̀ wọn ni àwọ̀n tí wọ́n dẹ sílẹ̀ kọ́.

Ka pipe ipin Sáàmù 9