Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 9:2-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Inú mi yóò dùn èmi yóò sì yọ̀ nínú Rẹ;Èmi o kọrin ìyìn sí orúkọ Rẹ, Ìwọ Ọ̀gá-Ògo jùlọ.

3. Àwọn ọ̀ta mi pẹ̀yìndà;Wọ́n kọsẹ̀ wọn sì ṣègbé níwájú Rẹ.

4. Nítorí ìwọ ti di òtítọ́ àti ọ̀ràn mi mú;ìwọ ti jókòó lórí ìtẹ́ Rẹ, láti ṣe ìdájọ́ òdodo.

5. Ìwọ ti bá orílẹ̀ èdè wí, Ìwọ sì ti pa ẹni búburú run;Ìwọ ti yọ orúkọ wọn kúrò láé àti láéláé.

6. Ìparun àìlópin ti borí àwọn ọ̀ta,Ìwọ ti fa àwọn ìlú wọn tu;Àní ìrántí wọn sì ti sègbé.

7. Olúwa jọba títí láé;ó ti gbé ìtẹ́ Rẹ̀ kalẹ̀ fún ìdájọ́.

8. Òun yóò sì ṣe ìdájọ́ àyé ní òdodo;yóò ṣe àkóso ènìyàn pẹ̀lú òdodo.

9. Olúwa ni ààbò fún àwọn tí a ni lára,ibi ìsádi ní àkókò ìpọ́njú.

10. Àwọn tí ó mọ orúkọ Rẹ yóò gbà ọ́ gbọ́,èmi tàbí ìwọ, Olúwa, kò kọ àwọn to ń wa a sílẹ̀.

11. Kọ orin ìyìn sí Olúwa, ti o ń jọba ní Síónì;kéde láàrin àwọn orílẹ̀ èdè ohun tí o ṣe.

12. Nítorí ẹni tí ó ń gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ rántí;òun kò kọ ẹkún àwọn tí a pọ́n lójú.

13. Olúwa, wo bí àwọn ọ̀ta ṣe ń ṣe inúnibíni sí mi!Ṣàánú, kí o sì gbé mí sókè kúrò ní ẹnu ọ̀nà ikú,

14. Kí èmi kí o lè sọ ti ìyìn Rẹni ẹnu ọ̀nà àwọn ọmọbìnrin Síónìàti láti máa yọ̀ nínú ìgbàlà Rẹ.

15. Àwọn orílẹ̀ èdè ti jìn sí kòtò ti wọn ti gbẹ́;ẹsẹ̀ wọn ni àwọ̀n tí wọ́n dẹ sílẹ̀ kọ́.

16. A mọ Olúwa nípa òdodo Rẹ̀;àwọn ènìyàn búburú ni a dẹ́kun mú nípa iṣẹ́ ọwọ́ wọn.

17. Àwọn ènìyàn búburú ni a ó dà sí isà òkú,àti gbogbo orílẹ̀ èdè tí ó gbàgbé Ọlọ́run.

18. Ṣùgbọ́n àwọn aláìní ni a ò ní gbàgbé láéláé,ìrètí àwọn ti ó talakà lójú kí yóò ṣègbé láéláé.

Ka pipe ipin Sáàmù 9