Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 89:4-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Èmi ó fi ìdí irú ọmọ Rẹ múlẹ̀ títí láéèmí ó sì máa gbe ìtẹ́ Rẹ ró láti ìran dé ìran”.

5. Àwọn ọ̀run yóò mú yín ṣiṣẹ́ ìyanu Rẹ, Olúwa,òtítọ́ Rẹ ní ìpéjọpọ̀ àwọn ẹni mímọ́.

6. Ta ní ó wà ni ọ̀run ti a lè fi we Olúwa?Ta ni nínú àwọn ọmọ alágbára ti a lè fi wé Olúwa?

7. Nínú àjọ ìgbìmọ̀ ẹni mímọ́, wọn bẹ̀rù Ọlọ́run gidigidi;ó sì ní ibùyìn fún jú gbogbo àwọn tí ó yí i ká.

8. Olúwa Ọlọ́run alágbára, ta ló dàbí Rẹìwọ jẹ́ alágbára, Olúwa, òtítọ́ Rẹ sì yí ọ ká.

9. Ìwọ ń darí ríru omi òkun;nígbà tí ó ru àwọn omi sókè, ìwọ mú wọn pa rọ́rọ́.

10. Ìwọ ni o ti ya Ráhábù pẹ́rẹpẹ̀rẹbí ẹni tí a pa;ìwọ ti fi apá ọwọ́ agbára Rẹtú àwọn ọ̀tá Rẹ ká.

11. Tìrẹ ní àwọn ọ̀run, ayé pẹ̀lú jẹ tìrẹ:ayé àti ohun gbogbo tí ó wà nínú Rẹ̀:ìwọ ti gbé wọn kalẹ̀.

12. Gúṣù àti Àríwá ìwọ ní ó dá wọn;Taborí àti Hámónì ń fi ayọ̀ yìn orúkọ Rẹ.

13. Ìwọ ní apá agbára;agbára ní ọwọ́ Rẹ, gíga ní ọwọ́ ọ̀tún Rẹ.

14. Òdodo àti òtítọ́ ní ìpílẹ̀ ìtẹ́ Rẹ:ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ àti òtítọ́ ń lọ ṣíwájú Rẹ.

15. Ìbùkún ní fún àwọn ènìyàn tí wọn mọ igbe ayọ̀,tí ó ń rìn Olúwa nínú ìmọ́lẹ̀ oju Rẹ.

16. Wọn ń ṣògo nínú orúkọ Rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́,wọn ń yin òdodo Rẹ.

17. Nítorí ìwọ ni ògo agbára wọn;nípa ojúrere ni ìwọ wá ń ṣògo.

18. Nítorí tí Olúwa ni asà wa,ọba wa sì ni Ẹni Mímọ́ Ísírẹ́lì.

19. Nígbà náà ní ìwọ sọ̀rọ̀ nínú ìran sí àwọn olótítọ́ Rẹ, wí pé:“èmi tí gbé adé kálẹ̀ sórí ẹni tí ó lágbára,èmi ti gbé ẹni tí a yan láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn ga.

20. Èmi tí rí Dáfídì ìránṣẹ́ mi;pẹ̀lú òróró mímọ́ mi ní mo fi yàn án;

21. Ìgbà gbogbo ni ọwọ́ mi yóò máa wà pẹ̀lú Rẹ̀a pá mí yóò sì fi agbára fún un.

22. Àwọn ọ̀tá kí yóò borí Rẹ̀,àwọn ènìyàn búburú kì yóò Rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀

23. Èmi yóò run àwọn ọ̀tá Rẹ níwájú Rẹèmi yóò lu àwọn tí ó kóríra Rẹ bolẹ̀

Ka pipe ipin Sáàmù 89