Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 89:31-51 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

31. Tí wọn bá kọ ìlànà mití wọ́n kò sì pa àṣẹ mi mọ́,

32. Nígbà náà ni èmi o fì ọ̀gà bẹ irékọjá wọn wòàti ẹ̀ṣẹ̀ wọn pẹ̀lú ìná:

33. Ṣùgbọ́n èmi kò ní mú ìfẹ́ mi tí ó dúró ṣinṣin kúrò lọ́dọ̀ Rẹ,tàbí ṣẹ́ tán sí òtítọ́ mi.

34. Èmi kì yóò sẹ́ májẹ̀mú mí,tàbí kí èmi yí ọ̀rọ̀ tí o ti ẹnu mi jáde padà.

35. Lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo ní èmi ti fi ìwà mímọ́ mi búra;èmi kì yóò purọ́ fún Dáfídì.

36. Irú ọmọ Rẹ yóò dúró títí láé,àti ìtẹ́ Rẹ̀ yóò dúró bí òòrùn níwájú mi.

37. A ó fi múlẹ̀ títí láé bí òṣùpá,àti bi ẹlẹ́rìí òtítọ́ ni ọ̀run”. Sela

38. Ṣùgbọ́n nísinsìnyí ìwọ ti sá tì, ìwọ sì kórìíra;ìwọ kún fún ìrunú sí ẹni àmì òróró Rẹ.

39. Ìwọ tì sọ májẹ̀mú ìránṣẹ́ Rẹ di òfo;ìwọ tàbùkù adé Rẹ nínú ilẹ

40. Ìwọ tí wo gbogbo àwọn odi Rẹ̀ìwọ sọ ibi gíga Rẹ̀ di ahoro.

41. Àwọn tí ń kọjá lọ fi ṣe ìjẹ;o ti di ẹ̀gàn àwọn olùbágbé e Rẹ̀

42. Ìwọ ti gbé ọwọ́ ọ̀tún ọ̀tá Rẹ̀ sókè;ìwọ mú gbogbo ọ̀tá Rẹ̀ yọ̀.

43. Pẹ̀lú, ìwọ ti yí ojú idà Rẹ̀ padà,ìwọ kò sì dúró tì í nínú ogun.

44. Ìwọ ti mú ògo Rẹ̀ kùnà,ìwọ si wó ìtẹ́ Rẹ̀ palẹ̀ sílẹ̀ẹ́lẹ̀.

45. Ìwọ ti gé ọjọ́ èwé Rẹ̀ kúrú;ìwọ si fi ìtìjú bò ó

46. Yóò ti pẹ́ tó, Olúwa?Tí ìwọ ó ha fi ara Rẹ pamọ́ títí láé?Yóò ti pẹ́ to tí ìbínú Rẹ yóò máa jó bí iná?

47. Rántí bí ọjọ́ mi ti kúrú tónítorí asán ha ní ìwọ fi sẹ̀dá àwọn ènìyàn!

48. Ta ni yóò wà láàyè tí kò ní rí ìkú Rẹ̀?Ta lo lé sa kúrò nínú agbára isà-òkú?

49. Olúwa, níbo ni ìṣeun ìfẹ́ Rẹ̀ àtijọ́ wà,tí ìwọ ti fi òtítọ́ Rẹ̀ búra fún Dáfídì?

50. Rántí, Olúwa, bí àti ń gan àwọn ìránṣẹ́ Rẹ;bí èmi ti gbà ní àyà mi láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn,

51. Ẹ̀gàn tí àwọn ọ̀tá Rẹ gàn, Olúwa,tí wọn gan ipaṣẹ̀ Ẹni àmì òróró Rẹ.

Ka pipe ipin Sáàmù 89