24. Òtítọ́ mi àti ìdúróṣinṣin ìfẹ́ yóò wà pẹ̀lú Rẹàti ní orúkọ mi ní a ó gbé ìwo Rẹ ga.
25. Èmi o gbé ọwọ́ Rẹ lórí òkunàti ọwọ́ ọ̀tún Rẹ lórí àwọn odo ńlá
26. Òun yóò kígbe sí mi pé, ‘ìwọ ní bàbá mi, Ọlọ́run mi, àti àpáta ìgbàlà mi!’
27. Èmi yóò ṣe é ni àkọ́bí mí,Ẹni gíga jù àwọn ọba ayé.
28. Títí láé ni èmi yóò pa ìfẹ́ dídúró ṣinṣin mọ́ fún un,àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú Rẹ̀ yóò dúró gbọingbọin.
29. Èmi o fi ìdí irú ọmọ Rẹ̀ múlẹ̀ títí láé,àti ìtẹ́ Rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀run ti wà láé.
30. “Bí àwọn ọmọ Rẹ̀ bá kọ òfin mi sílẹ̀tí wọ́n kò sì rìn gẹ́gẹ́ bí ìlànà mi.
31. Tí wọn bá kọ ìlànà mití wọ́n kò sì pa àṣẹ mi mọ́,
32. Nígbà náà ni èmi o fì ọ̀gà bẹ irékọjá wọn wòàti ẹ̀ṣẹ̀ wọn pẹ̀lú ìná:
33. Ṣùgbọ́n èmi kò ní mú ìfẹ́ mi tí ó dúró ṣinṣin kúrò lọ́dọ̀ Rẹ,tàbí ṣẹ́ tán sí òtítọ́ mi.