Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 89:21-30 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

21. Ìgbà gbogbo ni ọwọ́ mi yóò máa wà pẹ̀lú Rẹ̀a pá mí yóò sì fi agbára fún un.

22. Àwọn ọ̀tá kí yóò borí Rẹ̀,àwọn ènìyàn búburú kì yóò Rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀

23. Èmi yóò run àwọn ọ̀tá Rẹ níwájú Rẹèmi yóò lu àwọn tí ó kóríra Rẹ bolẹ̀

24. Òtítọ́ mi àti ìdúróṣinṣin ìfẹ́ yóò wà pẹ̀lú Rẹàti ní orúkọ mi ní a ó gbé ìwo Rẹ ga.

25. Èmi o gbé ọwọ́ Rẹ lórí òkunàti ọwọ́ ọ̀tún Rẹ lórí àwọn odo ńlá

26. Òun yóò kígbe sí mi pé, ‘ìwọ ní bàbá mi, Ọlọ́run mi, àti àpáta ìgbàlà mi!’

27. Èmi yóò ṣe é ni àkọ́bí mí,Ẹni gíga jù àwọn ọba ayé.

28. Títí láé ni èmi yóò pa ìfẹ́ dídúró ṣinṣin mọ́ fún un,àti májẹ̀mú mi pẹ̀lú Rẹ̀ yóò dúró gbọingbọin.

29. Èmi o fi ìdí irú ọmọ Rẹ̀ múlẹ̀ títí láé,àti ìtẹ́ Rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀run ti wà láé.

30. “Bí àwọn ọmọ Rẹ̀ bá kọ òfin mi sílẹ̀tí wọ́n kò sì rìn gẹ́gẹ́ bí ìlànà mi.

Ka pipe ipin Sáàmù 89