Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 89:11-21 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Tìrẹ ní àwọn ọ̀run, ayé pẹ̀lú jẹ tìrẹ:ayé àti ohun gbogbo tí ó wà nínú Rẹ̀:ìwọ ti gbé wọn kalẹ̀.

12. Gúṣù àti Àríwá ìwọ ní ó dá wọn;Taborí àti Hámónì ń fi ayọ̀ yìn orúkọ Rẹ.

13. Ìwọ ní apá agbára;agbára ní ọwọ́ Rẹ, gíga ní ọwọ́ ọ̀tún Rẹ.

14. Òdodo àti òtítọ́ ní ìpílẹ̀ ìtẹ́ Rẹ:ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ àti òtítọ́ ń lọ ṣíwájú Rẹ.

15. Ìbùkún ní fún àwọn ènìyàn tí wọn mọ igbe ayọ̀,tí ó ń rìn Olúwa nínú ìmọ́lẹ̀ oju Rẹ.

16. Wọn ń ṣògo nínú orúkọ Rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́,wọn ń yin òdodo Rẹ.

17. Nítorí ìwọ ni ògo agbára wọn;nípa ojúrere ni ìwọ wá ń ṣògo.

18. Nítorí tí Olúwa ni asà wa,ọba wa sì ni Ẹni Mímọ́ Ísírẹ́lì.

19. Nígbà náà ní ìwọ sọ̀rọ̀ nínú ìran sí àwọn olótítọ́ Rẹ, wí pé:“èmi tí gbé adé kálẹ̀ sórí ẹni tí ó lágbára,èmi ti gbé ẹni tí a yan láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn ga.

20. Èmi tí rí Dáfídì ìránṣẹ́ mi;pẹ̀lú òróró mímọ́ mi ní mo fi yàn án;

21. Ìgbà gbogbo ni ọwọ́ mi yóò máa wà pẹ̀lú Rẹ̀a pá mí yóò sì fi agbára fún un.

Ka pipe ipin Sáàmù 89