Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 88:2-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Jẹ́ kí àdúrà mi kí o wá sí iwájú Rẹ;dẹ etí Rẹ̀ sí igbe mi.

3. Nítorí ọkàn mi kún fún ìpọ́njúọkàn mi sì súnmọ́ isà òkú.

4. A kà mí mọ́ àwọn tí wọ́n lọ sí ọ̀gbun ilẹ̀èmi dà bí ọkùnrin tí kò ni agbára.

5. A yà mí sọ́tọ̀ pẹ̀lú àwọn òkúbí ẹni tí a pa tí ó dùbúlẹ̀ ní ipò ikú,ẹni tí ìwọ kò rántí mọ́,ẹni tí a gé kúrò lára àwọn tí ìwọ ń tọ́jú.

6. Ìwọ tí ó fi mí sí kòtò jínjìn,ní ibi ọ̀gbun tó ṣókùnkùn.

7. Ìbínú Rẹ ṣubú lé mi gidigidi;ìwọ ti fi àwọn ìjì Rẹ̀ borí mi.

8. Ìwọ tí gba ọ̀rẹ́ mi tí ó súnmọ́ mí kúrò lọ́wọ́ miìwọ sì sọ mi di ìríra sí wọn.A há mi mọ́, èmi kò sì lé è jáde;

9. Ojú mi káànú nítorí ìpọ́njú.Mo kígbe pè ọ́, Olúwa, ní gbogbo ọjọ́;mo na ọwọ́ mí jáde sí ọ.

10. Ìwọ ó fi iṣẹ́ ìyanu Rẹ hàn fún òkú?Àwọn òkú yóò ha dìde láti yín ọ́ bí?

11. A ó ha fi iṣeun ifẹ́ Rẹ hàn ni ibojì bí:Tàbí òtítọ́ Rẹ ni ipò iparun?

12. A ha le mọ iṣẹ́ ìyanu Rẹ ní òkùnkùn bíàti òdodo Rẹ ní ìlà ìgbàgbé?

13. Ṣùgbọ́n mo kígbe sí ọ fún ìrànlọ́wọ́, Olúwa;ní òwúrọ̀ ní àdúrà mí wá sọ́dọ̀ Rẹ.

14. Olúwa, èéṣe tí ìwọ fi kọ̀ mítí ìwọ fi ojú Rẹ pamọ́ fún mi?

15. Láti ìgbà èwe mi, ìṣẹ́ ń ṣẹ́ mi,èmi múra àti kú;nígbà ti ẹ̀ru Rẹ ba ń bà mí,èmi di gbére-gbère

16. Ìbínú Rẹ ti kọjá lára mi;ìbẹ̀rù Rẹ ti ge mi kúrò

Ka pipe ipin Sáàmù 88