9. Ṣe sí wọn bí ìwọ ti ṣe sí Mídíánìbí o ti ṣe sí Sísérà àti Jábínì ní òdò Kíṣíónì,
10. Ẹni tí ó ṣègbé ní Éndórítí wọn sì dàbí ààtàn ní orí ilẹ̀.
11. Ṣe àwọn ọlọ́lá wọn bí Orébù àti Séébù,àwọn ọmọ aládé wọn bí Ṣébà àti Sálmúnà,
12. Tí ó wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a gbà ní ìníẸni pápá oko tútù Ọlọ́run.”
13. Ìwọ Ọlọ́run, Ṣe wọn bí ààjà,bí ìyàngbò níwájú afẹ́fẹ́.
14. Bí ìna ti i jó ìgbẹ́ ìgbóàti bí ọ̀wọ́ iná ti ń mú òkè-ńlá gbiná,
15. Bẹ́ẹ̀ ni kí o fi ẹ̀fúùfù líle Rẹ lépa wọnja wọn lójú pẹ̀lú ìjì Rẹ