Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 81:8-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. “Gbọ́, ẹ̀yin ènìyàn mi, èmi ó sì kìlọ̀ fún un yín,bí ìwọ bá fetí sí mi, ìwọ Ísírẹ́lì.

9. Ẹ̀yin kì yóò ní Ọlọ́run ilẹ̀ mìíràn láàrin yín;ẹ̀yin kì yóò foríbalẹ̀ fún Ọlọ́run àjèjì.

10. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run Rẹ,ẹni tí ó mú un yín jáde láti Éjíbítì.Ẹ la ẹnu yín gbòòrò, èmi yóò sì kún un.

11. “Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi kì yóò gbọ́ tèmi;Ísírẹ́lì kò ní tẹríba fún mi.

12. Nítorí náà ni mo ṣe fi wọ́n fún ọkàn líle wọnláti máa rìn ní ọ̀nà ẹ̀tàn wọn.

13. “Bí àwọn ènìyàn mi yóò bá gbọ́ tèmibí Ísírẹ́lì yóò bá tẹ̀lé ọ̀nà mi,

14. Ní kánkán ni èmi yóò ṣẹ́gun àwọn ọ̀tá wọnkí ń sì yí ọwọ́ mi padà sí ọ̀tá wọn!

15. Àwọn tí ó kórìíra Olúwa yóò tẹríba níwájú Rẹ̀.Ìjìyà wọn yóò sì pẹ́ títí láé

16. Ṣùgbọ́n a ó fi ọkà tí ó dára bọ́ ọ́ yínèmi ó tẹ́ ẹ yín lọ́rùn pẹ̀lú oyin inú àpáta.”

Ka pipe ipin Sáàmù 81