2. Ẹ mú orin mímọ́, kí ẹ sì mú ìlù wátẹ dùùrù dídùn pẹ̀lú ohun èlò orin mímọ́.
3. Ẹ fún ìpè ni oṣù tuntunàní nígbà ti a yàn;ní ọjọ́ àjọ wa ti ó ni ìrònú.
4. Èyí ni àṣẹ fún Ísírẹ́lì,àti òfin Ọlọ́run Jákọ́bù.
5. Ó fi múlẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìlànà fún Jósẹ́fùnígbà tí ó la ìlẹ̀ Éjíbítì jáníbi tí a ti gbọ́ èdè tí kò yé wa.
6. Ó wí pé, “Mo gbé àjàgà kúro ní èjìká yín,a tú ọwọ́ wọn sílẹ̀ kúrò nínú apẹ̀rẹ̀.
7. Nínú ìnilára ni ẹ pè mo sì gbà yín là,mo dá a yín lóhùn nínú ìkọ̀kọ̀ àrá,mo dán an yín wò ní odò Méríbà. Sela
8. “Gbọ́, ẹ̀yin ènìyàn mi, èmi ó sì kìlọ̀ fún un yín,bí ìwọ bá fetí sí mi, ìwọ Ísírẹ́lì.
9. Ẹ̀yin kì yóò ní Ọlọ́run ilẹ̀ mìíràn láàrin yín;ẹ̀yin kì yóò foríbalẹ̀ fún Ọlọ́run àjèjì.