Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 81:1-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Kọrin sókè sí Ọlọ́run agbára waẸ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọ́run Jákọ́bù!

2. Ẹ mú orin mímọ́, kí ẹ sì mú ìlù wátẹ dùùrù dídùn pẹ̀lú ohun èlò orin mímọ́.

3. Ẹ fún ìpè ni oṣù tuntunàní nígbà ti a yàn;ní ọjọ́ àjọ wa ti ó ni ìrònú.

4. Èyí ni àṣẹ fún Ísírẹ́lì,àti òfin Ọlọ́run Jákọ́bù.

5. Ó fi múlẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìlànà fún Jósẹ́fùnígbà tí ó la ìlẹ̀ Éjíbítì jáníbi tí a ti gbọ́ èdè tí kò yé wa.

6. Ó wí pé, “Mo gbé àjàgà kúro ní èjìká yín,a tú ọwọ́ wọn sílẹ̀ kúrò nínú apẹ̀rẹ̀.

7. Nínú ìnilára ni ẹ pè mo sì gbà yín là,mo dá a yín lóhùn nínú ìkọ̀kọ̀ àrá,mo dán an yín wò ní odò Méríbà. Sela

8. “Gbọ́, ẹ̀yin ènìyàn mi, èmi ó sì kìlọ̀ fún un yín,bí ìwọ bá fetí sí mi, ìwọ Ísírẹ́lì.

9. Ẹ̀yin kì yóò ní Ọlọ́run ilẹ̀ mìíràn láàrin yín;ẹ̀yin kì yóò foríbalẹ̀ fún Ọlọ́run àjèjì.

10. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run Rẹ,ẹni tí ó mú un yín jáde láti Éjíbítì.Ẹ la ẹnu yín gbòòrò, èmi yóò sì kún un.

Ka pipe ipin Sáàmù 81