Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 80:6-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Ìwọ sọ wá di ẹlẹ́yà fún àwọn aládùúgbò wa,àwọn ọ̀tá wa sì ń yọ̀ wá.

7. Tún wa yípadà, ìwọ, Ọlọ́run;jẹ́ kí ojú Rẹ tàn sí wa,kí a ba à le gbà wá là.

8. Ìwọ mú àjàrà jáde láti Éjíbítì;ìwọ lé àwọn aláìkọlà jáde, o sì gbìn-ín.

9. Ìwọ sí àyè sílẹ̀ fún un,ìwọ sì mu tọ gbòǹgbò jìnlẹ̀ó sì kún ilẹ̀ náà.

10. A bò àwọn òkè mọ́lẹ̀ òkè pẹ̀lú òjijì Rẹ̀,ẹ̀ka Rẹ dàbí kédárì Ọlọ́run.

11. O yọ ẹ̀ka Rẹ̀ sínú òkun,ọwọ́ Rẹ̀ sí odò ńlá nì.

12. Èéṣe tí ìwọ fi wó odi Rẹ̀tí àwọn ènìyàn tí ó ń kọjá fi ń sa èso Rẹ̀?

13. Ìmọ̀do láti inú igbó ń bàá jẹ́àti ẹranko igbó ń jẹ ẹ́ run.

Ka pipe ipin Sáàmù 80