Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 80:5-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Ìwọ ti fi oúnjẹ bọ́ wọnìwọ ti mú wọn wa ẹ̀kún mu ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́

6. Ìwọ sọ wá di ẹlẹ́yà fún àwọn aládùúgbò wa,àwọn ọ̀tá wa sì ń yọ̀ wá.

7. Tún wa yípadà, ìwọ, Ọlọ́run;jẹ́ kí ojú Rẹ tàn sí wa,kí a ba à le gbà wá là.

8. Ìwọ mú àjàrà jáde láti Éjíbítì;ìwọ lé àwọn aláìkọlà jáde, o sì gbìn-ín.

9. Ìwọ sí àyè sílẹ̀ fún un,ìwọ sì mu tọ gbòǹgbò jìnlẹ̀ó sì kún ilẹ̀ náà.

10. A bò àwọn òkè mọ́lẹ̀ òkè pẹ̀lú òjijì Rẹ̀,ẹ̀ka Rẹ dàbí kédárì Ọlọ́run.

11. O yọ ẹ̀ka Rẹ̀ sínú òkun,ọwọ́ Rẹ̀ sí odò ńlá nì.

12. Èéṣe tí ìwọ fi wó odi Rẹ̀tí àwọn ènìyàn tí ó ń kọjá fi ń sa èso Rẹ̀?

13. Ìmọ̀do láti inú igbó ń bàá jẹ́àti ẹranko igbó ń jẹ ẹ́ run.

14. Yípadà sí wa, àwa ń bẹ̀ ọ, Ọlọ́run!Bo jú wolẹ̀ láti ọ̀run kí o sì wò ó!Kí o sì bẹ àjàrà yìí wò,

15. Gbòngbò èyí tí ọwọ́ ọ̀tún Rẹ ti gbìn,àti ẹ̀ka tí ìwọ ti mú lágbára fún ara Rẹ.

16. A gé àjàrà Rẹ lulẹ̀, a ti fi iná sun ún;ní ìfibú, àwọn ènìyàn Rẹ̀ ń ṣègbé.

17. Jẹ́ kí ọwọ́ Rẹ kí ó wà lára ọkùnrin tí ó wà ní ọwọ́ ọ̀tún Rẹ,ọmọ ènìyàn tí ìwọ tí gbékalẹ̀ fún ara Rẹ.

18. Nígbà náà àwa kí yóò yípadà kúrò lọ́dọ̀ Rẹ;mú wa yè, àwa o sì máa pe orúkọ Rẹ.

19. Tún wa yípadà, Olúwa Ọlọ́run;kí ojú Rẹ̀ kí o tan ìmọ́lẹ̀ sí wa,kí á ba à lè gbà wá là.

Ka pipe ipin Sáàmù 80