Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 80:2-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Níwájú Éfúremù, Bẹ́ńjámínì àti Mánásè.Rú agbára Rẹ̀ sókè;wa fún ìgbàlà wa.

3. Mú wa padà bọ̀ sípò, ìwọ Ọlọ́run;jẹ́ kí ojú Rẹ kí ó tan ìmọ́lẹ̀ sí wa,kí a bà lé gbà wá là

4. Olúwa Ọlọ́run,ìbínú Rẹ̀ yóò ti pẹ́ tósí àdúrà àwọn ènìyàn Rẹ?

5. Ìwọ ti fi oúnjẹ bọ́ wọnìwọ ti mú wọn wa ẹ̀kún mu ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́

6. Ìwọ sọ wá di ẹlẹ́yà fún àwọn aládùúgbò wa,àwọn ọ̀tá wa sì ń yọ̀ wá.

7. Tún wa yípadà, ìwọ, Ọlọ́run;jẹ́ kí ojú Rẹ tàn sí wa,kí a ba à le gbà wá là.

8. Ìwọ mú àjàrà jáde láti Éjíbítì;ìwọ lé àwọn aláìkọlà jáde, o sì gbìn-ín.

9. Ìwọ sí àyè sílẹ̀ fún un,ìwọ sì mu tọ gbòǹgbò jìnlẹ̀ó sì kún ilẹ̀ náà.

10. A bò àwọn òkè mọ́lẹ̀ òkè pẹ̀lú òjijì Rẹ̀,ẹ̀ka Rẹ dàbí kédárì Ọlọ́run.

11. O yọ ẹ̀ka Rẹ̀ sínú òkun,ọwọ́ Rẹ̀ sí odò ńlá nì.

Ka pipe ipin Sáàmù 80