62. Ó fi àwọn ènìyàn Rẹ̀ lé idà lọ́wọ́,ó sì bínú sí àwọn ohun ìní Rẹ̀.
63. Iná run àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn,àwọn ọmọbìnrin wọn kò sì ní orin ìgbéyàwó:
64. A fi àlùfáà wọn fún idà,àwọn opó wọn kò sì le è sunkún.
65. Olúwa sì jí gẹ́gẹ́ bí ẹni ojú oorun,gẹ́gẹ́ bí ọkùnrin ti i jù kúrò nínú ìraníyè ọtí.
66. Ó kọlu àwọn ọta Rẹ̀ padà;ó fí wọn sínú ìtìjú ayérayé.
67. Nígbà náà ni ó kọ́ àgọ́ Jósẹ́fù,kò sì yan ẹ̀yà Éfúráímù;
68. Ṣùgbọ́n ó yan ẹ̀yà Júdà,òkè Síónì, èyí tí ó fẹ́ràn.
69. Ó kọ́ ibi mímọ́ Rẹ̀, ibí gíga,gẹ́gẹ́ bí ayé tí ó fi ìdí Rẹ̀ múlẹ̀ títí láé.
70. Ó yan Dáfídì ìránṣẹ́ Rẹ̀ó mú láti inú àwọn agbo ẹran;
71. Ó mú un jáde nínú ìtọ́jú àgùntànláti jẹ́ olùṣọ́ Àgùntàn àwọn ènìyàn Rẹ̀ Jákọ́bùàti Ísírẹ́lì ogún un Rẹ̀.
72. Dáfídì sì ṣọ wọn pẹ̀lú òtítọ́ inú ọkàn;pẹ̀lú ọwọ́ òye ní ó fi darí wọn.