Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 78:60-69 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

60. Ó kọ àgọ́ Ṣílò sílẹ̀,àgọ́ tí ó ti gbé kalẹ̀ láàrin àwọn ènìyàn.

61. Ó rán àpótí ẹ̀rí, agbára Rẹ̀ lọ sí ìgbèkùn,dídán ògo Rẹ̀ lọ sí ọwọ́ àwọn ọ̀tá.

62. Ó fi àwọn ènìyàn Rẹ̀ lé idà lọ́wọ́,ó sì bínú sí àwọn ohun ìní Rẹ̀.

63. Iná run àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn,àwọn ọmọbìnrin wọn kò sì ní orin ìgbéyàwó:

64. A fi àlùfáà wọn fún idà,àwọn opó wọn kò sì le è sunkún.

65. Olúwa sì jí gẹ́gẹ́ bí ẹni ojú oorun,gẹ́gẹ́ bí ọkùnrin ti i jù kúrò nínú ìraníyè ọtí.

66. Ó kọlu àwọn ọta Rẹ̀ padà;ó fí wọn sínú ìtìjú ayérayé.

67. Nígbà náà ni ó kọ́ àgọ́ Jósẹ́fù,kò sì yan ẹ̀yà Éfúráímù;

68. Ṣùgbọ́n ó yan ẹ̀yà Júdà,òkè Síónì, èyí tí ó fẹ́ràn.

69. Ó kọ́ ibi mímọ́ Rẹ̀, ibí gíga,gẹ́gẹ́ bí ayé tí ó fi ìdí Rẹ̀ múlẹ̀ títí láé.

Ka pipe ipin Sáàmù 78