Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 78:36-53 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

36. Ṣùgbọ́n nígbà náà ni wọ́n yóò pọ́n-ọn pẹ̀lú ẹnu wọ́nwọ́n fí ahọ́n wọ́n purọ́ fún un;

37. Ọkàn wọn kò sòtítọ́ si i,wọn kò jẹ́ olódodo sí májẹ̀mú Rẹ̀.

38. Ṣíbẹ̀ ó ṣàánú;ó dárí àìṣedédé wọn jìnòun kò sì pa wọn runnígbà kí ì gbà ló ń dá ìbínú Rẹ̀ dúrókò sì rú ìbínú Rẹ̀ sókè

39. Ó ránti pé ẹlẹ́ran ara ni wọ́n,afẹ́fẹ́ tó ń kọjá tí kò le padà.

40. Nígbà gbogbo ní wọn ń ṣọ̀tẹ̀ síi ní ihàwọn mú-un bínú nínú ilẹ̀ tí ó di ahoro!

41. Síwájú àti síwájú wọn dán Ọlọ́run wò;wọ́n mú ẹni mímọ́ Ísírẹ́lì bínú.

42. Wọ́n kò rántí agbára Rẹ̀:ní ọjọ́ tí ó rà wọ́n padà lọ́wọ́ àwọn aninilára,

43. Ní ọjọ́ tí ó fi iṣẹ́ ìyanu Rẹ̀ hàn ní Éjíbítì,àti iṣẹ́ àmì Rẹ ni ẹkùn Sáónì

44. Ó ṣọ omi wọn dí ẹ̀jẹ̀;wọn kò le mú láti odò wọn.

45. Ó rán ọ̀wọ́ ẹṣinṣin láti pa wọ́n run,àti ọpọlọ tí ó bá wọn jẹun.

46. Ó fi ọkà wọn fún láńtataàwọn irè oko wọn fún eṣú

47. Ó fi yìnyín ba àjàrà wọn jẹ́ó bá èso sìkàmore wọn jẹ́

48. Ó fi ohun ọ̀sìn wọn fún yìnyínagbo ẹran wọn fún mọ̀nàmọ́ná

49. Ó mú kíkorò ìbínú Rẹ̀ wá sí wọn lára,ìrunú àti ikáánú, àti ìpọ́njú,nípa rírán ańgẹ́lì apanirun sí wọn.

50. Ó pèṣè ipa fún ìbínú Rẹ̀òun kò gbà wọ́n lọ́wọ́ ikúṣùgbọ́n ó fi ẹ̀mí wọ́n fún àjàkálẹ̀-àrùn

51. Ó kọlu àwọn àkọ́bí ọmọ ọkùnrin ÉjíbítìOlórí agbára wọn nínú àgọ́ Ámù

52. Ṣùgbọ́n ó mú àwọn ènìyàn Rẹ̀ jáde bí ọ̀wọ́ ẹran;ó sọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí àgùntàn nínú ihà.

53. Ó dáàbòbò wọ́n dáadáa, nítorí náà ni ẹ̀rù kò ṣe bà wọ́nṣùgbọ́n òkun padé mọ́ àwọn ọ̀tá wọn.

Ka pipe ipin Sáàmù 78