Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 78:31-36 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

31. Ìbínú Ọlọ́run dìde sí wọnó pa àwọn tí ó jùlọ nínú wọn,ó sì lu àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Ísírẹ́lì bolẹ̀.

32. Nínú gbogbo ìwọ̀nyí, wọn ń sá síwájú;nínú gbogbo iṣẹ́ ìyanu Rẹ̀, wọ́n kò gbàgbọ́

33. O fi òpin sí ayé wọn nínú asánàti ọdún wọn nínú ìpayà.

34. Nígbà kígbà tí Ọlọ́run bá pa wọ́n,wọn yóò wá a kirì;wọn yóò fi ìtara yípadà sí i.

35. Wọ́n rántí pé Ọlọ́run ní àpáta wọn;wí pé Ọlọ́run ọ̀gá ògo jùlọ ni olùràpadà àpáta wọn

36. Ṣùgbọ́n nígbà náà ni wọ́n yóò pọ́n-ọn pẹ̀lú ẹnu wọ́nwọ́n fí ahọ́n wọ́n purọ́ fún un;

Ka pipe ipin Sáàmù 78