Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 78:3-17 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Ohun tí a ti gbọ́ tí a sì ti mọ̀,ohun tí àwọn baba wa ti sọ fún wa.

4. Àwa kí yóò pa wọ́n mọ́kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọmọ,ní fífí ìyìn Olúwa, àti ipa Rẹ̀àti iṣẹ́ ìyanu tó ti ṣe hànfún ìran tí ń bọ̀.

5. Ó gbé ẹ̀rí kalẹ̀ ní Jákọ́bùo sì fìdí àṣẹ múlẹ̀ ní Ísírẹ́lì,èyí tí ó páláṣẹ fún àwọn baba ńlá waláti kọ́ àwọn ọmọ wọn,

6. Nítorí náà àwọn ìran tí ń bọ̀ yóò mọ̀ wọ́nbẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ tí a kò tí i bítí yóò dìde ti wọn yóò sọ fún àwọn ọmọ wọn

7. Nígbà náà ni wọn o fi ìgbẹ̀kẹ̀lé wọn sínú Ọlọ́runwọn kò sì ní gbàgbé iṣẹ́ Ọlọ́runṣùgbọ́n wọn o pa àṣẹ Rẹ̀ mọ́.

8. Wọn ò ní dàbí àwọn baba ńlá wọnìran aláyà líle àti ọlọ́tẹ̀tí ọkàn wọn kò sòòtọ̀ si oloore.

9. Àwọn ọkùnrin Éfúráímù, tí ó há mọ́ ọ tí wọ́n mú ọrun,wọ́n yípadà ní ọjọ́ ogun

10. Wọ́n kò pa májẹ̀mú Ọlọ́run mọ́wọn sì kọ̀ láti máa gbé nínú òfin Rẹ̀

11. Wọ́n gbàgbé ohun tí ó ti ṣe,àwọn ìyanu tí ó ti fi hàn wọ́n.

12. O ṣe ìyanu níwájú àwọn baba wọn ní ilẹ̀ Éjíbítì, ní agbégbé Síónì

13. O pín òkun níyà, ó sì mú wọn kọjáó mù kí ó nà dúró bá ebè

14. Ní ọ̀ṣán ó fi ìkúùku àwọsánmọ̀ ṣe amọ̀nà wọnàti ní gbogbo òru pẹ̀lú, ìmọ̀lẹ̀ ìná.

15. Ó sán àpáta ní ihàó si fún wọn ní omi mímu lọ́pọ̀lọpọ̀bí ẹni pé láti inú ibú wá.

16. O mú ìṣàn omi jáde láti inú àpátaomi sìṣsàn sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí odò

17. Wọ́n sì tún tẹ̀ṣíwájú láti dẹ́sẹ̀ sí iní ìsọ̀tẹ̀ sí Ọ̀gá ògo ní àgìnjú.

Ka pipe ipin Sáàmù 78