Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 72:5-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Àwọn òtòsì àti aláìníyóò máa fi ọ̀wọ̀ ńlá fún ọ nígbà gbogbo,níwọ̀n ìgbà tí oòrùn àti òṣùpá bá ń ràn,yóò ti pẹ́ tó,láti ìran díran.

6. Yóò dàbí òjò tí o ń rọ̀ sórí pápá ìrẹ́mọ́lẹ̀Bí ọwọ́ òjò tó ń rin ilẹ̀

7. Àwọn olódodo yóò gbilẹ̀ ni ọjọ́ Rẹ̀ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà yóò sì wà;títí tí oṣùpá kò fi ní sí mọ́

8. Yóò máa jọba láti òkun dé òkunàti láti odò títí dé òpin ayé.

9. Àwọn tí ó wà ní ihà yóò tẹríba fún unàwọn ọ̀ta Rẹ̀ yóò máa lá erùpẹ̀ ilẹ̀.

10. Àwọn ọba Táṣíṣì àti tí erékùṣùwọn yóò mú ọrẹ wá fún un;àwọn ọba Ṣéba àti Síbàwọn o mú ẹ̀bùn wá fún-un.

11. Gbogbo ọba yóò tẹríba fún-unàti gbogbo orílẹ̀ èdè yóò sìn ín.

12. Nítorí yóò gba àwọn aláìnínígbà tí ó bá ń ké,tálákà àti ẹní tí kò ni olùrànlọ́wọ́.

13. Yóò káànú àwọn aláìlera àti aláìníyóò pa aláìní mọ́ kúrò nínú ikú.

Ka pipe ipin Sáàmù 72