Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 72:16-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. Kí ìkúnwọ́ ọkà wà lórí ilẹ̀;ní orí òkè ni kí ó máa dàgbàkí èso Rẹ̀ kí o gbilẹ̀ bí ti Lébánónìyóò máa gbá yìn-ìn bí koríko ilẹ̀.

17. Kí orúkọ Rẹ̀ kí o wà títí láé;orúkọ Rẹ̀ yóò máa gbilẹ̀ níwọn bí òòrùn yóò ti pẹ́ tó;wọn ó sì máa bùkún fún ara wọn nipaṣẹ̀ Rẹ.Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ní yóò máa pè mí ní alábùkún fún.

18. Olùbùkún ní Olúwa Ọlọ́run, Ọlọ́run Ísírẹ́li,ẹnìkan ṣoṣo tí ó n ṣe ohun ìyanu.

19. Olùbùkun ni orúkọ Rẹ tí ó lógo títí láé;kí gbogbo ayé kún fún ògo Rẹ.Àmín àti Àmín.

20. Èyí ni ìpàrí àdúrà Dáfídì ọmọ Jéṣè.

Ka pipe ipin Sáàmù 72