Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 71:8-16 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Ìyìn Rẹ̀ kún ẹnu mi,o ń sọ ti ọlá Rẹ̀ ní ọjọ́ gbogbo.

9. Má ṣe ta mí nù ni ọjọ́ ogbó miMá ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ nígbà tí kò sí okun mọ́

10. Nítorí àwọn ọ̀tá mi ń sọ̀rọ̀ òdì sí miàwọn tí wọn dúró láti pa mí gbìmọ̀ pọ̀

11. Wọ́n wí pé, “Ọlọ́run ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀;lépa Rẹ̀ kí ẹ sì munítorí kò sí ẹni tí yóò gbà á.”

12. Má ṣe jìnnà sí mi, Ọlọ́run;wa kánkán, Ọlọ́run mi, láti rànmí lọ́wọ́.

13. Jẹ́ kí wọn kí ó dààmúkí a sì run àwọn tí ń ṣe ọ̀tá ọkàn mikí a sì fi ẹ̀gàn àti àbùkùbò àwọn tí ń wá ìpalára mi.

14. Ṣùgbọ́n ní tèmí, ìgbà gbogbo ní ìrètí mi;èmi ó yìn ọ́ síwájú àti síwájú sì i.

15. Ẹnu mí yóò sọ nípa ti òdodo Rẹ,ti ìgbàlà Rẹ ni gbogbo ọjọ́lóòtọ́, èmi kò mọ́ iye Rẹ̀.

16. Èmi ó wá láti wá kéde agbára Olúwa Ọlọ́run;èmi ó kéde òdodo Rẹ̀ nìkan.

Ka pipe ipin Sáàmù 71