Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 71:5-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Nítorí ìwọ jẹ́ ìrètí mi, Olúwa Ọlọ́run,ìwọ ni ìgbẹ́kẹ̀lé mí láti ìgbà èwe

6. Mo gbẹ́kẹ̀lé ọ láti ìgbà ìbí mi;Ìwọ mu mi jáde láti inú ìyá mi wáèmi ó máa yìn ọ títí láé

7. Mo di ẹni ìyanu fún ọ̀pọ̀ ènìyàn,ṣùgbọ́n ìwọ ni ààbò mi tí ó lágbára.

8. Ìyìn Rẹ̀ kún ẹnu mi,o ń sọ ti ọlá Rẹ̀ ní ọjọ́ gbogbo.

9. Má ṣe ta mí nù ni ọjọ́ ogbó miMá ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ nígbà tí kò sí okun mọ́

10. Nítorí àwọn ọ̀tá mi ń sọ̀rọ̀ òdì sí miàwọn tí wọn dúró láti pa mí gbìmọ̀ pọ̀

Ka pipe ipin Sáàmù 71