Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 71:17-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Láti ìgbà èwe, Ọlọ́run ni ìwọ tí kọ́ mítítí di òní ni mo ń sọ ti iṣẹ́ ìyanu Rẹ̀.

18. Pẹ̀lúpẹ̀lú, nígbà tí ẹnu di arúgbó tán tí mo sì hewú,Má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀, Ọlọ́runtítí tí èmi o fi ipá re han ìran yìíàti agbára Rẹ fún gbogbo àwọn aráẹ̀yìn, sọ ti agbára sí ìran tí ń bọ̀agbára Rẹ̀ fún àwọn tí yóò wá.

19. Ọlọ́run, Òdodo Rẹ̀ dé ọ̀run,ìwọ tí ó ti ṣe ohun ńláTa ni, Ọlọ́run, tí o dà bí i Rẹ?

20. Pẹ̀lúpẹ̀lú ìwọ ti mú mi rí ìdààmú, tí o pọ̀ tí ó sì korò,ìwọ yóò tún sọ ayé mi jíìwọ yóò sì tún mú mi sọ sókèláti ọ̀gbun ilẹ̀ wá.Ìwọ yóò sọ ọlá mi di púpọ̀

21. Ìwọ yóò fi kún ọwọ́ miìwọ yóò tù mí nínú ní hà gbogbo.

22. Èmi yóò fi dùùrù mi yìnfún òtítọ́ Rẹ, Ọlọ́run mi;èmi ó kọrin ìyìn sí ọ pẹ̀lú dùùrùìwọ ẹni mímọ́ Ísírẹ́lì.

23. Ètè mi yóò kígbe fún ìyìnnígbà tí mo bá kọrín ìyìn sí ọ:èmi, ẹni tí o ràpadà.

24. Ahọ́n mí yóò sọ ti òdodo Rẹ ní gbogbo ọjọ́,fún àwọn tí ó fẹ́ pa mí láraa sì dójúti àwọn tí ń wá ìdààmú mi.

Ka pipe ipin Sáàmù 71