Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 7:1-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Olúwa Ọlọ́run mi, ààbò mi wà nínú Rẹ;gba mí là kí o sì tú mí sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn tó ń lé mi,

2. kí wọn ó má bá à fa ọkàn mi ya gẹ́gẹ́ bí kìnnìúnwọn a ya á pẹ́rẹpẹ̀rẹ láìsí ẹni tí yóò gba mí.

3. Olúwa Ọlọ́run mi, tí èmi bá ṣe èyítí ẹ̀bi sì wà ní ọwọ́ mi

4. Bí èmi bá ṣe ibi sí ẹni tí ń wá àlàáfíà pẹ̀lú mití mo ja ọ̀ta mí lólè láìnídìí:

5. Nígbà náà jẹ́ kí ọ̀ta mi le mi kí wọn sì mú mi;jẹ́ kí òun kí ó tẹ ẹ̀mí mi mọ́lẹ̀kí wọn sì mú mi sùn nínú eruku. Sela

6. Dìde, Olúwa, nínú ìbínú Rẹ;dìde lòdì sí ìrunú àwọn ọ̀ta mi.Jí, Ọlọ́run mi; kéde òdodo.

7. Kí ìpéjọ àwọn ènìyàn yí ká.Jọba lórí wọn láti òkè wá;

8. Jẹ́ kí Olúwa ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn.ṣe ìdájọ́ mi, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òdodo mi,gẹ́gẹ́ bí ìwà òtítọ́, ẹni gíga jùlọ.

9. Ọlọ́run Olódodo,Ẹni tí ó ń wo inú àti ọkàn,tí ó ń mú òpin sí ìwà ipá ẹni búburútí ó sì ń pa àwọn olódodo mọ́.

10. Aṣà mi ní Ọlọ́run tí ó gajù,ẹni tí ń dáàbò bo àwọn ẹni gíga nípa ti èmi.

11. Ọlọ́run ni onídàájọ́ tòótọ́,Ọlọ́run tí ń sọ ìrúnú Rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́.

12. Bí kò bá yípadà,òun yóò pọ́n idà Rẹ̀ múó ti fa ọrun Rẹ̀ le náó ti múra Rẹ̀ sílẹ̀

13. Ó ti pèṣè ohun ìjà ikú sílẹ̀;ó ti pèṣè ọfà iná sílẹ̀.

14. Ẹni tí ó lóyún ohun búburú,tí ó sì lóyùn wàhálà ó bí èké jáde.

15. Ẹni tí ó gbẹ́ ọ̀fìn, tí ó kó o jádejìn sí kòtò tí ó gbẹ́ sílẹ̀.

Ka pipe ipin Sáàmù 7