Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 69:18-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

18. Súnmọ́ tòsí kí ó sì gbà mí là;rà mí padà nítorí àwọn ọ̀ta mi.

19. Ìwọ tí mọ ẹ̀gàn mi, ìtìjú mi àti àìlọ́lá;Gbogbo àwọn ọ̀ta mi wà níwájú Rẹ̀.

20. Ẹ̀gàn ba ọkàn mi jẹ́ wọ́n fi mí sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́Mo ń wá aláàánú, ṣùgbọ́n kò sí,mo ń wá olùtùnú, Ṣùgbọ́n n kò rí ẹnìkankan.

21. Wọ́n fi òróró fún mi pẹ̀lú ohun jíjẹ mi,àti ní òungbẹ mi, wọn fi ọtí kíkan fún mi.

22. Jẹ́ kí tábìlì wọn kí ó dí ìkẹ́kùnni iwájú wọn, kí ó sì di okùn dídẹfún àwọn tó wà ní àlàáfíà.

23. Kí ojú wọn kií ó ṣókùnkùn kí wọ́n má ṣe ríran,kí eyín wọn di títẹ̀ títí láé.

24. Tú ìbínú Rẹ jáde sí wọn;kí ìbínú gbígbóná Rẹ bò wọ́n mọ́lẹ̀.

25. Kí ibùjókòó wọn di ahoro;kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé nínú wọn.

26. Nítorí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí ẹni tí ìwọ ti lù,àti ìrora àwọn tí ó ti ṣèṣe

Ka pipe ipin Sáàmù 69