Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 68:22-35 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

22. Olúwa wí pé, “Èmi o mú wọn wá láti Báṣánì;èmi ó mú wọn wá láti ibú omi òkun,

23. Kí ẹṣẹ̀ Rẹ̀ kí ó le pọ́n ní inú ẹ̀jẹ̀ àwọn ọ̀tá Rẹ̀,àti ahọ́n àwọn ajá Rẹ̀ ní ìpín ti wọn lára àwọn ọ̀tá Rẹ.”

24. Wọn ti rì ìrìn Rẹ, Ọlọ́run,irin Ọlọ́run mi àti ọba mi ní ibi mímọ́ Rẹ̀.

25. Àwọn akọrin ní íwájú,tí wọn ń lu tanborí

26. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa ní ẹgbẹgbẹ́;àní fún Olúwa ẹ̀yin tí ó ti orísun Ísírẹ́lì wá.

27. Níbẹ̀ ní ẹ̀yà kékeré Bẹ́ńjámínì wà, tí o ń darí wọn,níbẹ̀ ni àwọn ọmọ aládé Júdà,níbẹ̀ ni àwọn ọmọ aládé Sébúlúnì àti tí Náfútàlì.

28. Pàsẹ agbára Rẹ, Ọlọ́run;fi agbára Rẹ hàn wá, Ọlọ́run, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe tẹ́lẹ̀.

29. Nítorí tẹ́ḿpìlì Rẹ ni Jérúsálẹ́mùàwọn ọba yóò mú ẹ̀bùn wá fún ọ.

30. Bá àwọn ẹranko búburú wí,tí ń gbé láàrin ìkoọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn akọ màlúùpẹ̀lú àwọn ọmọ màlúùtítí olúkúlùkù yóò fi forí balẹ̀ pẹ̀lú ìwọn fàdákà:tú àwọn orílẹ̀-èdè ti ń ṣe inú dídùn si ogun ká

31. Àwọn ọmọ aládé yóò wá láti Éjíbítì;Jẹ́ kí Etiópíà na ọwọ́ Rẹ̀ sí Ọlọ́run.

32. Kọrin sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ìjọba ayé,kọrin ìyìn sí Olúwa, Sela

33. Sí ẹni tí ń gún ọ̀run dé ọ̀run àtijọ́ lókè,tó ń fọhùn Rẹ̀, ohùn ńlá.

34. Kéde agbára Ọlọ́run,ọlá ńlá Rẹ̀ wà lórí Ísírẹ́lìtí agbára Rẹ̀ wà lójú ọ̀run.

35. Ìwọ ní ẹ̀rù, Ọlọ́run, ní ibi mímọ́ Rẹ;Ọlọ́run Ísírẹ́lìfi agbára àti òkun fún àwọn ènìyàn Rẹ̀.Olùbùkún ní Ọlọ́run!

Ka pipe ipin Sáàmù 68