Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 68:17-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ní kẹ̀kẹ́ ogun Ọlọ́runẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún; Olúwa ń bẹ láàrin wọn ní Sínáì ni ibi mímọ́ Rẹ̀.

18. Ìwọ ti gòkè sí ibi gígaìwọ ti di ìgbèkùn ní ìgbékùn lọ;ìwọ ti gbà ẹ̀bùn fún ènìyàn:nítòótọ́, fún àwọn ọlọ̀tẹ̀ pẹ̀lú,Kí Olúwa Ọlọ́run lè máa bá wọn gbé.

19. Olùbùkún ni Ọlọ́run,sí Ọlọ́run Olùgbàlà wa,ẹni tí ó ń fi ojojúmọ́ gba ẹrù wa rù. Sela

20. Ọlọ́run wa jẹ́ Ọlọ́run tó ń gbàlààti sí Olúwa Ọlọ́run ni ó ń gbà wá lọ́wọ́ ikú.

21. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò tẹ orí àwọn ọ̀tá Rẹ̀,àti agbárí onirun àwọn tó ń tẹ̀ṣíwájú nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn

22. Olúwa wí pé, “Èmi o mú wọn wá láti Báṣánì;èmi ó mú wọn wá láti ibú omi òkun,

Ka pipe ipin Sáàmù 68