Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 66:3-14 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Ẹ wí fún Ọlọ́run “pé,ìwọ ti ní ẹ̀rù tó nínú iṣẹ́ Rẹ̀!Nípa ọ̀pọ̀ agbára Rẹ ni àwọn ọ̀táRẹ yóò fi sìn ọ́.

4. Gbogbo ayé ń wólẹ̀ fún ọ;wọn ń kọrin ìyìn sí ọ,wọ́n ń kọrin ìyìn sí orúkọ Rẹ.” Sela

5. Ẹ wá wo ohun tí Ọlọ́run ṣe,Iṣẹ́ Rẹ̀ ti ní ẹ̀rù tó sí àwọn ọmọ ènìyàn!

6. O yí òkun padà sí ilẹ̀ gbígbẹ,wọ́n fi ẹsẹ̀ rìn inú omi kọjá,níbẹ̀ ni àwa yọ̀ nínú Rẹ.

7. O ń jọba títí láé nípa agbára Rẹ̀,ojú Rẹ̀ ń wò orílẹ̀ èdèkí àwọn ọlọ̀tẹ̀ má ṣe gbé ara wọn ga. Sela

8. Ẹ yin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn,jẹ́ kí a mú ni gbọ́ ohun ìyìn Rẹ̀;

9. O ti dá ààbò bo ẹ̀mí wakò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ wa kí o yẹ̀

10. Nítorí ìwọ, Ọlọ́run, Dan wa wò;ìwọ dán wa bí a tí ń Dan fàdákà wo

11. Ìwọ mú wa wá sínú ẹ̀wọ̀no sì di ẹ̀rù lé ẹ̀yìn wa

12. Ìwọ mú àwọn ènìyàn gun wá ní oríàwa la iná àti omi kọjáṣùgbọ́n ìwọ mú wa dé ibi ọ̀pọ̀.

13. Èmi ó wá sí tẹ́ḿpìlì Rẹ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísunkí n sì mú ẹ̀jẹ́ mi ṣẹ sí ọ

14. Ẹ̀jẹ́ ti ètè mi jẹ́, tí ẹnu mi sì sọnígbà tí mo wà nínú ìsòro.

Ka pipe ipin Sáàmù 66