Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 66:13-20 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

13. Èmi ó wá sí tẹ́ḿpìlì Rẹ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísunkí n sì mú ẹ̀jẹ́ mi ṣẹ sí ọ

14. Ẹ̀jẹ́ ti ètè mi jẹ́, tí ẹnu mi sì sọnígbà tí mo wà nínú ìsòro.

15. Èmi o sun ẹbọ ọlọ́ràá sí ọàti ẹbọ ọ̀rá àgbò;èmi o rú akọ màlúù àti ewúrẹ́. Sela

16. Ẹ wá gbọ́ gbogbo ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Olúwa;ẹ jẹ́ kí n sọ ohun tí ó ṣe fún mi.

17. Mo fi ẹnu mi kígbe sókè sí i:Ìyìn Rẹ̀ wà ní ẹnu mi.

18. Bí èmi bá gba ẹ̀ṣẹ̀ ní àyà mi, Olúwa kì yóò gbọ́ ohùn mi;

19. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run gbọ́ nítòótọ́o ti gbọ́ ohun mi nínú àdúrà.

20. Ìyìn ni fún Ọlọ́runẹni tí kò kọ àdúrà mitàbí mú ìfẹ́ Rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi!

Ka pipe ipin Sáàmù 66