Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 65:4-13 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Ìbùkún ni fún àwọn tí o yàntí o mú wa láti máa gbé àgọ́ Rẹ!A tẹ wá lọ́rùn pẹ̀lú ohun rere inú ilé Rẹ,ti tẹ́ḿpìlì mímọ́ Rẹ.

5. Ìwọ dá wa lóhùn pẹ̀lú ohùn ìyanu ti òdodo,Ọlọ́run olùgbàlà wa,ìrètí gbogbo òpin ayéàti àwọn tí ó jìnnà nínú òkun,

6. Ìwọ tí ó dá òkè nípa agbára Rẹtí ó di ara Rẹ̀ ní àmùrè agbára

7. Ẹni tí ó mú ríru omi òkun dákẹ́ríru ariwo omi wọn,àti gìdìgìdì àwọn ènìyàn

8. Àwọn tí ó ń gbé òkèrè bẹ̀rù agbára Rẹ̀:ìwọ mú ìjáde òwúrọ̀ àti ti àṣálẹ̀ yọìwọ pé orin ayọ̀ jáde.

9. Ìwọ bẹ ayé wò, o sì bomirin;ìwọ mú ní ọ̀rọ̀ púpọ̀.Ọ̀dọ̀ Ọlọ́run kún fún omiláti pèsè ọkàn fún àwọn ènìyàn,nítorí ibẹ̀ ní ìwọ ti yàn án.

10. Ìwọ fi ìrinmi sí aporo Rẹìwọ tẹ́ ògúlùtù Rẹ;ìwọ fi òjò mú ilẹ̀ Rẹ rọ̀o sì bùkún ọ̀gbìn Rẹ.

11. Iwọ fi oore Rẹ de ọdún ni adé,ọ̀rá ń kan ni ipa-ọ̀nà Rẹ

12. Pápá-tútù ni ihà ń kán: àwọn òkè kékèké fi ayọ̀ di ara wọn ni àmùrè.

13. Agbo ẹran ni a fi wọ pápá tútù náà, ni asọ; àfonífojì ni a fi ọkà bò mọ́lẹ̀,wọn hó fún ayọ̀, wọn ń kọrin pẹ̀lú.

Ka pipe ipin Sáàmù 65