Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 64:5-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Wọ́n, gba ara wọn níyànjú nínú èrò búburú,wọ́n sọ̀rọ̀ lórí dídẹ́kun sílẹ̀ ní kọ̀kọ̀wọ́n wí pé, “Ta ni yóò rí wa?”

6. Wọ́n gbìmọ̀ àìsòdodo, wọn wí pé,“A wa ti parí èrò tí a gbà tán”lóòtọ́ àyà àti ọkàn ènìyàn kún fún àrékérekè.

7. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò ta wọ́n ní ọfà;wọn ó sì gbọgbẹ́ lójijì.

8. Ahọ́n wọn yóò sì dojú ìjà kọ wọ́n, yóò sì run wọ́nGbogbo ẹni tí ó bá rí wọn yóò sì mi orí fún wọn.

9. Gbogbo ènìyàn yóò máa bẹ̀rùwọn ó kéde iṣẹ́ Ọlọ́runwọn ó dúró lé ohun tí ó ṣe.

10. Jẹ́ kí Olódodo kí o yọ̀ nínú Olúwayóò sì rí ààbò nínú Rẹ̀Gbogbo ẹni ìdúró ṣinṣin ni àyà yóò máa yìn ín.

Ka pipe ipin Sáàmù 64