Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 62:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Nínú Ọlọ́run nìkan ni ọkàn mi ti rí ìsinmi;ìgbàlà mi ti ọ̀dọ̀ Rẹ̀ wá.

2. Òun nìkan ní àpáta mi àti ìgbàlà mi;oun ní ààbò mi, a kí yóò sí mi ní pò padà.

3. Ẹ̀yin ó ti máa rọ́lù ènìyàn kan pẹ́ tó?Gbogbo yín ni ó fẹ pa á,bí ògiri tí ó fẹ́ yẹ̀ àti bí ọgbà tí ń wó lọ?

4. Kìkì èró wọn ni láti bì ṣubúkúrò nínú ọlá Rẹ̀;inú wọn dùn sí irọ́.Wọn ń fi ẹnu wọn súre,ṣùgbọ́n wọ́n ń gégùn nínú ọkàn wọn. Sela

Ka pipe ipin Sáàmù 62