Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 60:3-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Ìwọ ti fi ìgbà ewu hàn àwọn ènìyàn Rẹ;Ìwọ fún wa ní wáìnì tí ó máa ń ta wa gbọ́n-ọ́ngbọ́n-ọ́n.

4. Àwọn tí ó bẹ̀rù Rẹ̀ ní ìwọ fi ọ̀págun fúnkí a lè fíhàn nítorí òtítọ́. Sela

5. Fi ọwọ́ ọ̀tún Rẹ̀ gbà wá kí ó sì ràn wá lọ́wọ́,kí a lè gba àwọn tí o fẹ́ là.

6. Ọlọ́run ti sọ̀rọ̀ láti ibi mímọ́ Rẹ̀:“Ní ayọ̀, èmi ó pín ṣèkémù jádeèmi o sì wọ̀n àfonífojì ṣúkótù.

7. Tèmi ni Gílíádì, tèmi sì ni Mánásè;Éfúráímù ni àsìbórì mi,Júdà sì ní ọ̀pá àṣẹ mi.

8. Móábù ní ìkòkò ìwẹsẹ̀ mi,lórí Édómù ní mo bọ́ bàtà mi sí;lórí fìlísitinì ni mo kígbe ayọ̀.”

9. Ta ni yóò mú mi wá sí ìlú olódi nì?Ta ni yóò tọ́ mí lọ sí Édómù?

10. Kí ha ń ṣe ìwọ, Ọlọ́run, tí ó ti kọ̀ wá sílẹ̀tí o kò sì bá ogun wa jáde mọ́?

11. Fún wa ní ìrànlọ́wọ́ lórí àwọn ọ̀tá,nítorí asán ní ìrànlọ́wọ́ ènìyàn.

12. Nípa Ọlọ́run ni a ó ní ìṣẹ́gun,yóò sì tẹ̀ àwọn ọ̀tá wa mọ́lẹ̀.

Ka pipe ipin Sáàmù 60