Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 6:2-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Ṣàánú fún mi, Olúwa, nítorí èmi ń ku lọ; Olúwa, wò mí sán, nítorí egungun mi wà nínú ìnira.

3. Ọkàn mi wà nínú ìrora.Yóò ti pẹ́ tó, Olúwa, yóò ti pẹ́ tó?

4. Yípadà, Olúwa, kí ó sì gbà mí;gbà mí là nípa ìfẹ́ Rẹ tí kì í ṣákìí.

5. Ẹnikẹ́ni kò sì rántí Rẹ nígbà tí ó bá kú.Ta ni yóò yìn ọ́ láti inú iṣà òkú?

6. Agara ìkérora mi da mi tán;gbogbo òru ni mo wẹ ibùsùn mi pẹ̀lú ẹkúnmo sì fi omi rin ibùsùn mi pẹ̀lú omijé.

7. Ojú mi di aláìlera pẹ̀lú ìbànújẹ́;wọ́n kùnà nítorí gbogbo ọ̀tá mi.

8. Kúrò lọ́dọ̀ mi, gbogbo ẹ̀yin tí ń ṣe iṣẹ́ ibi,nítorí Olúwa ti gbọ́ igbe mi.

9. Olúwa ti gbọ́ ẹkún mi fún àánú; Olúwa ti gba àdúrà mi.

10. Gbogbo àwọn ọ̀tá mi lójú yóò tì, wọn yóò sì dààmú;wọn yóò sì yípadà nínú ìtìjú àìròtẹ́lẹ̀.

Ka pipe ipin Sáàmù 6