Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 58:1-8 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ẹ̀yin ha ń sọ òdodo nítòotọ́ẹ̀yin ijọ ènìyàn?Ǹjẹ́ ẹ̀yìn ń ṣe ìdájọ́ tí ó ṣe títọ́ẹ̀yìn ọmọ ènìyàn?

2. Bẹ́ẹ̀ kọ́, nínú ọkàn yín ẹ̀yìn ń gbèrò àìsòdodo,Ọmọ yín sì tú ìwà ipá jáde ni ayé.

3. Ní inú ìyá wọn wá, ni eniyàn búburú tí sìnà lojukan náà tí a ti bí wọnwọn a máa ṣèké.

4. Ọ̀rọ̀ wọn dà bí ọ̀rọ̀ ejò,gẹ́gẹ́ bí ti sèbé tí ó dítí Rẹ̀,wọn dàbí adití ejò paramọ́lẹ̀ tí ó di ara Rẹ̀ ni etí

5. Tí kò ní gbọ́ ìpè àwọn atinilójú,bí ó ti wù kí ó máa fi ọgbọ́n ṣe ìtujú tó.

6. Ká eyín ẹnu wọn, Ọlọ́run;ní ẹnu wọnká ọ̀gan àwọn ọmọ kìnnìún, Olúwa.

7. Jẹ́ kí wọn parẹ́ bí omi tó ń ṣàn lọ;nígbà tí ó bá fa ọfà Rẹ̀, kí ọ̀kọ̀ wọn kí ó ṣẹ́.

8. Jẹ́ kí wọn rí bí ìgbín tí Rẹ̀ dànù tí ó sì ṣègbébí ọmọ ti oṣu Rẹ̀ kò pé, kí wọn má ṣe rí òòrùn.

Ka pipe ipin Sáàmù 58