Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 55:8-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Èmi ìbá yára lọ́ si ibùgbé mi ní ibi ààbò,jìnnà kúrò nínú ìjì àti èfúùfù líle.”

9. Da àwọn ẹni búburú láàmú, Olúwa, da ahọ́n wọn rú,nítorí èmi rí ìwà agbára àti ìjà ní ìlú náà.

10. Ọ̀sán àti oru ní wọ́n fí ń rìn gbogbo odi kiri;àrankàn àti èébú wà láàrin Rẹ̀.

11. Ìwà búburú ń bẹ ní àárin Rẹ̀;ìdẹ́rùbà àti irọ́ kò kúrò ní ìgboro Rẹ̀.

12. Tí ọ̀tá bá tàbùkù mi,èmi yóò fara mọ́ ọn;tí ọ̀ta bá gbé ara Rẹ̀ ga sími,èmi ibá sá pamọ́ fún un.

13. Ṣùgbọ́n tí ó bá ṣe ìwọ, ọkùnrin bí ẹgbẹ́ mi,ẹlẹgbẹ́ mi, àti ọ̀rẹ́ tí ó sún mọ́ mi,

14. pẹ̀lú ẹni tí èmi ti jẹ ìgbádún adùn ìdàpọ̀bí a ṣe ń rìn pẹ̀lú àwujọ ní ilé Ọlọ́run.

15. Kí ikú kí ó dé bá wọn,Kí wọn ó lọ láàyè sí isà òkú,Jẹ́ kí wọn ó sọ̀kalẹ̀ sí ibojì pẹ̀lú ìpayà,nítorí tí ìwà búburú ń bẹ ní ibùjókòó wọn, àti nínú wọn.

16. Ṣùgbọ́n èmi pe Ọlọ́run; Olúwa yóò sì gbà mí.

17. Ní alẹ́, ní òwúrọ̀ àti ní ọ̀sánèmi sunkún jáde nínú ìpọ́njú,o sì gbọ́ ohùn mi.

18. Ó rà mí padà láìléwukúrò nínú ogun tí ó dìde sí mi,nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó dìde sí mi.

19. Ọlọ́run yóò gbọ́ yóò sì pọ́n wọn lójúàní, ẹni tí ó ti jókòó láti ìgbà a nì—SelaNítorí tí wọn kò ní àyípadà,tí wọn kò sì bẹ̀rù Ọlọ́run.

20. Ọ̀rẹ́ mi yìí ti dalẹ̀ èmi ọ̀rẹ́ Rẹ̀;ó ti bá májẹ̀mú Rẹ̀ jẹ́.

21. Ọ̀rọ̀ ẹnu Rẹ̀ kúnná ju òrí àmọ́,ṣùgbọ́n ogun ija wà ni àyà Rẹ̀;ọ̀rọ̀ Rẹ̀ fẹ́lẹ́ ju òróró lọ,ṣùgbọ́n idà fífà yọ ní wọn.

22. Gbé ẹrù Rẹ lọ sí ọ̀dọ̀ Olúwayóò sì mú ọ dúró;òun kò ní jẹ́ kí olódodo ṣubú.

23. Ṣùgbọ́n ìwọ, Ọlọ́run, ni yóò mu àwọn ọ̀tá miwá sí ihò ìparun;Àwọn ẹni tí òǹgbẹ ẹ̀jẹ̀ ń gbẹ àti ẹni ẹ̀tànkì yóò gbé ààbọ̀ ọjọ́ wọn.Ṣùgbọ́n fún èmi, èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ.

Ka pipe ipin Sáàmù 55