Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 50:5-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. “Kó àwọn ènìyàn mímọ́ jọ fún miàwọn tí wọn fi ẹbọ dá májẹ̀mú fún mi”.

6. Àwọn ọ̀run sọ̀rọ̀ òdodo Rẹ̀,Nítorí òun fúnrarẹ̀ ni onídàájọ́

7. Ẹ gbọ́, ẹ̀yin ènìyàn mi, èmi yóò si sọ̀rọ̀, ìwọ Ísírẹ́lì, èmi yóò jẹrìí sí ọ:èmi ní Ọlọ́run, àní Ọlọ́run Rẹ.

8. Èmi kí yóò bá ọ wínítorí àwọn ìrúbọ Rẹ̀tàbí ọrẹ̀ ẹbọ sísun Rẹ, èyí tí ó wà níwájú miní ìgbà gbogbo.

9. Èmí kò fẹ́ kí ó mú akọ màlúù láti inú ilé tí ó kọ fún untàbí kí o mú ewúré látiinú agbo ẹran Rẹ̀

10. Nítorí gbogbo ẹran igbó ni tèmíàti ẹran ọ̀sìn lórí ẹgbẹ̀rún òkè.

Ka pipe ipin Sáàmù 50