Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 50:1-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Olúwa, Ọlọ́run Alágbárasọ̀rọ̀ kí o sì pè ayé jọláti ìlà oorùn títí dé ìwọ̀ Rẹ̀.

2. Láti Síónì wá, pípé ni ẹwà,Ọlọ́run tí ń tan ìmọ́lẹ̀

3. Ọlọ́run ń bọ̀ bẹ́ẹ̀ ni kì yóò dákẹ́,iná yóò máa jó níwájú Rẹ̀,àti ní àyíká Rẹ̀ ni ẹ̀fúfù líle yóò ti máa jà ká.

4. Yóò sì pe àwọn ọ̀run láti òkè wá jọ àti ayé,kí o le máa ṣe ìdárò àwọn ènìyàn Rẹ̀.

5. “Kó àwọn ènìyàn mímọ́ jọ fún miàwọn tí wọn fi ẹbọ dá májẹ̀mú fún mi”.

6. Àwọn ọ̀run sọ̀rọ̀ òdodo Rẹ̀,Nítorí òun fúnrarẹ̀ ni onídàájọ́

7. Ẹ gbọ́, ẹ̀yin ènìyàn mi, èmi yóò si sọ̀rọ̀, ìwọ Ísírẹ́lì, èmi yóò jẹrìí sí ọ:èmi ní Ọlọ́run, àní Ọlọ́run Rẹ.

Ka pipe ipin Sáàmù 50