Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 44:7-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Ṣùgbọ́n ìwọ fún wa ní ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá wa,ìwọ sì ti dójúti àwọn tí ó kórìíra wa.

8. Nínú Ọlọ́run àwa ń ṣògo ní gbogbo ọjọ́,àwa ó sì yin orúkọ Rẹ̀ títí láé. Sela

9. Ṣùgbọ́n nísinsìnyí ìwọ ti kọ̀ wá, ìwọ sì ti dójútì wá;Ìwọ kò sì bá àwọn ọmọ ogun wa jáde mọ́.

10. Ìwọ ti bá wa jàìwọ sì ti ṣẹ́gun wa níwájú àwọn ọ̀tá wa,àwọn ọ̀ta wa ti gba ilẹ̀ wa,wọ́n sì fi ipá gba oko wa.

11. Ìwọ fi wá fún jíjẹ bí ẹran àgùntànÌwọ sì ti tú wa ká sí àárin àwọn aláìkọlà.

Ka pipe ipin Sáàmù 44