Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 44:19-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

19. Ṣùgbọ́n wọ́n kọ lù wá,ìwọ sì sọ wá di ẹran ọdẹ fún àwọn ajákotí wọn sì fi òkùnkùn biribiri bò wá mọ́lẹ̀.

20. Bí àwa bá ti gbàgbé orúkọ Ọlọ́run watàbí tí a na ọwọ́ wa sí ọlọ́run àjèjì.

21. Ǹjẹ́ Ọlọ́run kì yóò rí ìdí Rẹ̀,níwọ̀n ìgbà tí ó mọ ohun ìkọ̀kò inú ọkàn?

22. Ṣíbẹ̀, nítorí Rẹ̀ àwa da àyà kọ ikú, ní ojojúmọ́a ń kà wá sí bí àgùntàn fún pípa.

23. Jí, Olúwa! Èéṣe tí ìwọ ń sùn?Dìde fún ra Rẹ! Má ṣe kọ̀ wá sílẹ̀ láéláé.

24. Èéṣe tí ìwọ ń pa ojú Rẹ mọ́tí ìwọ sì gbàgbé ìpọ́njú àti ìnira wa?

25. Nítorí a tẹrí ọkàn wa ba sínú eruku;ara wa sì dì mọ́ erùpẹ̀ ilẹ̀.

26. Dìde kí o sì ràn wá lọ́wọ́;ràwápadà nítorí ìfẹ́ Rẹ tí ó dúró ṣinṣin.

Ka pipe ipin Sáàmù 44