Atijọ Majemu

Majẹmu Titun

Sáàmù 44:16-22 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. nítorí ọ̀rọ̀ ẹ̀gàn àti ọ̀rọ̀ ẹ̀tànní ojú àwọn ọ̀ta àti olùgbẹ̀san.

17. Gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí ń ṣẹlẹ̀ sí wa,ṣíbẹ̀ àwa kò gbàgbé Rẹ̀bẹ́ẹ̀ ni a kò ṣèké sí májẹ̀mu Rẹ̀.

18. Ọkàn wa kò padà sẹ́yìn;bẹ́ẹ̀ ni ẹsẹ̀ wa kò yẹ̀ kúrò ní ọ̀nà Rẹ̀.

19. Ṣùgbọ́n wọ́n kọ lù wá,ìwọ sì sọ wá di ẹran ọdẹ fún àwọn ajákotí wọn sì fi òkùnkùn biribiri bò wá mọ́lẹ̀.

20. Bí àwa bá ti gbàgbé orúkọ Ọlọ́run watàbí tí a na ọwọ́ wa sí ọlọ́run àjèjì.

21. Ǹjẹ́ Ọlọ́run kì yóò rí ìdí Rẹ̀,níwọ̀n ìgbà tí ó mọ ohun ìkọ̀kò inú ọkàn?

22. Ṣíbẹ̀, nítorí Rẹ̀ àwa da àyà kọ ikú, ní ojojúmọ́a ń kà wá sí bí àgùntàn fún pípa.

Ka pipe ipin Sáàmù 44